*Igbesẹ tuntun lati mu aabo orile-ede le, lati ja Boko Haram, bandit ati gbigbe eniyan
Orísun: OJB News Yoruba | Akọroyin: Olalekan Akanji Ademeto, Abuja | Olootu: Lekan Lawal | Ojú-òpó: OJB Media Hub | Ọjọ Ẹti, 24, Oṣù Keje 2026
Aare Bola Ahmed Tinubu ti fọwọ si atunto nla ninu Ẹṣọ Ologun Naijiria, pẹlu igbesoke iye ẹka ologun naa lati di ẹka mejila [12 Divisions] ati aṣẹ lati gba ọmọ ologun tuntun ẹgbẹrun mejidinlogbon wọle.[28]
Gẹgẹ bi eto tuntun naa, ẹka ologun mejila naa yoo wa ni:
1 Division – Kaduna, 2 Division – Ibadan, 3 Division – Jos, 5 Division – Makurdi, 6 Division – Port Harcourt, 7 Division – Maiduguri, 8 Division – Sokoto, 9 Division – Ilorin, 10 Division – Jalingo, 81 Division – Lagos, 82 Division – Enugu, ati 83 Division tuntun ni Benin City.
Eto naa yoo ṣe iranlọwọ lati bo gbogbo agbegbe orile-ede naa, fun ija lodi si Boko Haram, bandit, gbigbe eniyan, ati rudurudu abẹle.
Atunto naa yoo waye ni ipele meji. Ipele akọkọ ni didasile ẹka 5, 9, ati 10 ati atunto awọn ẹka to wa tẹlẹ, ti yoo pari ni Oṣu Kẹsan 2026. Ipele keji ni didasile ẹka 83 tuntun ni Benin City, ti yoo pari ni Oṣu Kejila 2026.
Awọn orisun ologun ni pe igbesoke naa yoo dinku wahala lori awọn ọmọ ologun to wa, yoo mu ki wọn yara de ibi isẹlẹ, ati lati mu aabo le ni awọn agbegbe ti wahala ti n ṣẹlẹ julọ. Yoo tun ṣẹda aye iṣẹ fun ẹgbẹẹgbẹrun ọdọ Naijiria.
Iroyin naa ti fa ariwo nla kaakiri orile-ede, ọpọlọpọ n gba igbesẹ naa gẹgẹ bi ohun ti o yẹ, nigba ti awọn miran n rọ ijọba lati pese owo to peye, ohun elo igbalode ati itọju to dara fun awọn ọmọ ologun ki eto naa le ṣe anfani gidi.
