KUNLE ADEGBITE GBÉ IGBESẸ OTUN LÁTI S’ATILEYIN FÚN ÈTÒ ÀBÒ

Orísun: OJB News Yoruba | Akọroyin: Muyideen Akinro, Ìbàdàn| Olootu: Lekan Lawal | Ojú-òpó: OJB Media Hub | Ọjọ Iṣẹgun, 8, Oṣù Kẹ̀sán 2026 | ojbmediashub.com.ng | +2348066952410

 

 

Dr. Kunle Samson Adegbite (TWINDAD), olùdíje fún ipò Aṣojú ní Ilé Ìgbìmọ̀ Aṣòfin Àpapọ̀ fún Ogbomoso North, Ogbomoso South àti Oriire, ti gbé ìgbésẹ̀ pàtàkì mìíràn láti fìdí múlẹ̀ ìfẹ́ rẹ̀ sí ààbò àti ìdàgbàsókè àwùjọ̀ wa.

 

Lónìí, ó fi mọ́tò alùpùpù (Yamaha) tuntun ṣe ẹ̀bùn fún ẹgbẹ́ Irú Ẹkun Security, ẹ̀ka Ogbomoso, láti mú kí iṣẹ́ wọn túbọ̀ lágbára àti láti mú kí ìrìnàjò wọn rọrùn nínú àwọn àdúgbò wa.

Dókítà Kunle Adegbite lásìkò to n fà Ọkàdá lè Oloye Sunday Adeyemo Igboho lọ́wọ́ pẹlu àlejò kan

Aṣáájú náà fi iṣẹ́ náà lé ẹgbẹ́ rẹ̀ lọ́wọ́ láti fi mọ́tò náà lé Chief Sunday Igboho, Olùdásílẹ̀ àti Alákóso Irú Ẹkun Security ní orílẹ̀-èdè Nàìjíríà lọ́wọ́.

ÌRÒYÌN ÌṢÁÁJÚ:

Eyii ni ìwúlò àti anfaani tí ọlọpaa àgbáyé tí ṣe fún orile-ede Naijiria gẹ́gẹ́ bí ọga àgbà Ọlọpa Tunde Disu ṣe sọ..

Ọba k’oba yòówù tí ó bá dá sí ọrọ òṣèlú yóò jẹ iyàn rẹ n’isu, eyii ni ikilọ tí Gómìnà Seyi Makinde ṣe lásìkò…

Nínú ọ̀rọ̀ rẹ̀, Dr. Adegbite sọ pé:

“Mo gbà gbọ́ gidigidi pé àṣáájú kì í ṣe ọ̀rọ̀ ẹnu àti ìlérí òṣèlú nìkan. Ó yẹ kí a fi hàn nípasẹ̀ àwọn ìgbésẹ̀ gidi tí ó ń dáhùn sí àìní àti ìṣòro àwọn ará wa. Ààbò jẹ́ ojúṣe gbogbo wa. Nítorí náà, ìrànlọ́wọ́ fún àwọn tí wọ́n fi ara wọn jìn láti dáàbò bo àwùjọ̀ wa jẹ́ ojúṣe tí ó ṣe pàtàkì sí mi pẹ̀lú.”

Ó tún ké sí àwọn aṣáájú àwùjọ, àwọn tó ń bójú tó ààbò, àwọn ilé-iṣẹ́, ẹgbẹ́ àjọ, àwọn aṣáájú òṣèlú àti gbogbo ẹni rere láti darapọ̀ mọ́ oún nínú mímú ètò ààbò le sí i ní orílẹ̀-èdè wa.

Dókítà Kunle Adegbite, Oloye Sunday Adeyemo Igboho àti àwọn ọmọ ẹgbẹ irú ẹkùn lákòókò ayẹyẹ òun

“A gbọ́dọ̀ ṣiṣẹ́ pọ̀ láti kọ́ àwùjọ tí àwọn ènìyàn wa lè gbé, ṣiṣẹ́, kí wọ́n sì lè ní ìlọsíwájú nínú àlàáfíà àti ààbò. Èyí ni irú àṣáájú tí mo gbà gbọ́ nínú rẹ̀ — àṣáájú tí ó ń gbọ́, tí ó ń dáhùn, tí ó sì ń gbé ìgbésẹ̀. Iṣẹ́ náà ṣì ń tẹ̀síwájú.”

 

Dr. Kunle Samson Adegbite (TWINDAD)

Olùdíje NDC fún Ogbomoso North, South & Oriire Federal Constituency

Ìṣẹ́ fún Aráyé. Ìfarajìn sí Ìdàgbàsókè.

One thought on “KUNLE ADEGBITE GBÉ IGBESẸ OTUN LÁTI S’ATILEYIN FÚN ÈTÒ ÀBÒ

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *

OJB MEDIA HUB is a premier online news platform delivering accurate, timely and unbiased new accross Nigeria and the world.