OWO RÈÉ IKÚ RÈÉ, IYAWO L’ANLỌỌ́DU FÚN MÍ NI FÀÌFUU MILIONU, KI N FÚN LÓYÚN

Orísun: OJB News Yorùbá | Onkotan: Aṣiwaju Olalekan Akanji Ademeto, Sango-Ọta | Olootu: Lekan Lawal | Ojú-òpó: OJB Media Hub | Ọjọbọ, 29, Oṣù Keje 2026.

 

Ìyàwó onílé mi ti ń ju pátá abẹ́ rẹ̀ sílẹ̀ lẹ́nu ọna ilẹ̀kùn mi láàárọ̀ gbogbo. Ṣùgbọ́n ní àná tí mo gbé padà e lọ sí yàrá rẹ̀ láti dá a padà fún un, ó ṣí ilẹ̀kùn, ó wọ ṣòkòtò ìwẹ̀ nìkan, ó wá sọ pé: “Mo ti ń retí rẹ, ọmọ mi.”

9

Gbogbo wàhálà yìí bẹ̀rẹ̀ lọ́sẹ̀ méjì sẹ́yìn. Láàárọ̀ kọ̀ọ̀kan ní aago márùn-ún àbọ̀, bí mo bá ṣí ilẹ̀kùn mi, pátá abẹ́ ìyàwó onílé mi ló máa wà lórí èèkàn ilẹ̀kùn.

 

Ó rò pé mi ò mọ̀ pé òun ni, ó rò pé màá sọ ọ́ sínú ilé ilẹ̀, ṣùgbọ́n mi ò ṣe bẹ́ẹ̀.

 

Dípò bẹ́ẹ̀, màá gbé e, máa sọ sínú àpò dúdú kan, kí n sì fi sá sínú abẹ́ tímutimu mi níbi tí ẹnikẹ́ni kò ní rí i.

 

Ṣùgbọ́n nígbà tí àpò náà kún pákú, ó ti sú mi, inú bí mi, ẹ̀rù sì bà mí. Mo wá so pé ó tó, kí n fi òpin sí ìwà òmùgọ̀ yìí.

 

Ní alẹ́ ọjọ́ náà, kíákíá bí mo ti rí ọkọ rẹ̀ tí ó wakọ̀ jáde kúrò ní àgbàlá, mo gbé àpò náà, mo sáré gùn òkè lọ sí yàrá rẹ̀. Mo ń yí ojú ká kiri láti rí i dájú pé ẹnikẹ́ni kò rí mi.

 

Nígbà tí mo kàn án ilẹ̀kùn, ọkàn mi ń lù gbim gbim gbim.

 

Ilẹ̀kùn ṣí gbàà. Níbẹ̀ ló dúró, ó wọ ṣòkòtò ìwẹ̀ nìkan, ara rẹ̀ sì ń tọ́ omi jàbúrúkú bí ẹni tí ó ṣẹ̀ṣẹ̀ jáde láti inú balùwẹ̀.

 

Ohun tó mú mi pà báàyì jù ni pé kò fara yà, kò sì gbìyànjú láti bo ara rẹ̀ dáadáa.

 

Mrs Cole wo mi lójú, ó sì sọ jẹ́ẹ́jẹ́ẹ́ pé: “Mo ti ń retí rẹ, ọmọ mi.”

 

Ọ̀fun mi gbẹ pátápátá, ara mi bẹ̀rẹ̀ sí í wárìrì.

 

Mo na ọwọ́ tí ń mì lùlù sí i láti fi àpò náà fún un, “Mádám ẹ gbà nǹkan yín, mi ò fẹ́ ìjà kankan.”

 

“Wá sí inú Joseph,” ó sọ, ó ń tọ́ka sí mi. “Jẹ́ kí n fi ibi tí o máa gbe e sí hàn ọ́.”

 

Gbogbo ohun tí mo fẹ́ ni kí n dá nǹkan rẹ̀ padà, ṣùgbọ́n ìyàwó onílé mi ń fa mi lọ títí tí mo fi dé yàrá rẹ̀.

 

“Joseph, wá gbe e sínú yàrá yìí, má bẹ̀rù.”

 

Ó rẹ́rìn-ín gidi, ó sì ṣí ilẹ̀kùn náà sílẹ̀ tó kí n lè rí inú yàrá náà gbangba.

 

Lọ́gán lọ́gán, ẹsẹ̀ mi di. Mi ò lè yẹra mọ́. Ó jókòó lẹ́gbẹ̀ẹ́ ibùsùn ni onílé mi, Mr. Cole.

 

Mo dáyá. Ṣé mò ṣẹ̀ṣẹ̀ rí i tí ó wakọ̀ jáde? Tàbí ẹlòmíràn ni?

 

“Wá sí inú, ọ̀dọ́kùnrin,” Mr. Cole sọ jẹ́ẹ́jẹ́ẹ́.

 

Orí dàrú mi, ẹ̀rù bà mí, mi ò sì gbàgbọ́ ojú mi. Mo wo ìyàwó rẹ̀ tí ó wọ ṣòkòtò ìwẹ̀ nìkan, mo tún wo òun. Ọwọ́ mi ń mì tóbẹ́ẹ̀ tí àpò náà fi bọ́ lulẹ̀.

 

“A ti ń ṣọ́ ọ fún oṣù mẹ́rin,” onílé mi sọ̀rọ̀, ó ń fi ọwọ́ pa irungbọ̀n rẹ̀. “Dókítà sọ pé mi ò lè bí mọ́, Mr Joseph. Mi ò lè fún ìyàwó mi lóyún, àwọn ẹbí mi sì ti ń halẹ̀ mọ́ ọn pé wọn máa lé e jáde kúrò nínú ilé yìí bí kò bá lóyún kí ọdún yìí tó lọ.”

 

Ìyàwó rẹ̀ ti ilẹ̀kùn lẹ́yìn mi pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́, ó sì tì í pa.

 

“A nílò ọkùnrin tí ó dakẹ́, tí ara rẹ̀ yá, tí ó sì lè pa ẹnu mọ́,” ó sọ, ó ń súnmọ́ mi díẹ̀díẹ̀.

 

Mr. Cole dìde, ó lọ sí kọ́bọ́dù aṣọ rẹ̀, ó fa àpò bíràwùn ńlá kan jáde, ó sì gbé e lé ibùsùn.

 

“Ìyẹn ni mílíọ̀nù márùn-ún naira,” onílé mi sọ, ó kọ ojú si mi. “Fún ìyàwó mi lóyún. Ẹ máa ṣe é níhìn-ín, lónìí. Èmi máa lọ jókòó ní pálọ̀ títí ẹ fi parí.”

 

Ẹ̀rù bà mí gidi, mi ò mọ̀rírì ohun tí ń ṣẹlẹ̀ mọ́. Kí n tó lè ya lẹ́nu, Mr. Cole ti jáde kúrò nínú yàrá náà, ó ti ilẹ̀kùn, ìyàwó rẹ̀ sì bẹ̀rẹ̀ sí í tú ṣòkòtò ìwẹ̀ rẹ̀ díẹ̀díẹ̀.

 

Ìtẹ̀síwájú ìṣẹ̀lẹ̀ yí ń bọ̀ laipẹ, ẹkù ojú lọ́nà

 

Follow the OJB MEDIA HUB channel on WhatsApp: https://whatsapp.com/channel/0029Va8RpCj8fewvCADtHd0K

 

Follow the OJB MEDIA HUB page, like and comment. click on the link below : https://www.facebook.com/oojiirebimediashub

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *

OJB MEDIA HUB is a premier online news platform delivering accurate, timely and unbiased new accross Nigeria and the world.