*Eegun Olóòlù yóò jade ní Ìbàdàn, obìnrin kò gbọdọ̀ fi ojú kan an – Oba Ladoja
Orísun: OJB News Yorùbá | Akọroyin: Muyideen Akinro, Ìbàdàn | Olootu: Lekan Lawal | Ojú-òpó: OJB Media Hub | Ọjọ Àìkú, 26, Oṣù Keje 2026
Olubadan ilu Ibadan, Oba Rasidi Adewolu Ladoja (Arusa I), ti kilọ fun gbogbo awọn obinrin ni ilu Ibadan ati agbegbe rẹ lati ṣọra gidigidi ni ọjọ Ajé ọsẹ ti n bọ.
Kabiesi, ninu ikilọ rẹ, sọ pe Eegun Olóòlù, eegun ibilẹ pataki ni ilu Ibadan, yoo jade laiyara ọjọ naa, nitori naa ko yẹ ki obinrin kankan fi oju kan an.
Gẹgẹ bi ọrọ Olubadan:
“Ẹyin obinrin, ẹ ṣọra yin lati ọjọ Ajé ti i ṣe Monday ọsẹ to n bọ. Eegun Olóòlù yoo jade ni Ibadan, obinrin ko si gbọdọ fi oju kan an rara.”
Oba Ladoja tẹnumọ pe ofin ibilẹ yii wa lati ọjọ pipẹ, ati pe o yẹ ki awọn obinrin tẹle e fun alaafia ati bọwọ fun aṣa ilu Ibadan.
