EYII NI ÌTÀN ÌGBÉSÍ AYÉ TAIWO HASSAN BABATUNDE OGOGO

Orísun: OJB News Yoruba | Akọroyin: Temitope Hafsat, Sango-Ọta | Olootu: Lekan Lawal | Ojú-òpó: OJB Media Hub | Ọjọ Iṣẹgun, 25, Oṣù Kẹjọ 2026 | ojbmediashub.com.ng | +2348066952410

 

*Ta ni Taiwo Hassan Ogogo?

 

Ọjọ kọkanlelọgbọn osu kẹwa ọdun 1959 ni wọn bi Taiwo Hassan, ti ọpọ eeyan mọ si Ogogo.

 

Ọmọbibi ilu Ilaro, to wa ni agbegbe Yewa nipinlẹ Ogun nii se, to si jẹ ibeji, tori ibeji ni wọn saba maa n bi ninu idile rẹ.

Bakan naa ni baba ati iya rẹ naa jẹ ibeji.

 

 

 

 

Ogogo pari ile ẹkọ alakọbẹrẹ rẹ nile ẹkọ Christ Church nilu Ilaro, ko to morile ile ẹkọ girama Gazikia College nilu Eko.

 

Amọ Ogogo ko le pari ile ẹkọ girama naa tori ọda owo, lẹyin naa lo wa lọ sile ẹkọ ẹkọsẹ ọwọ nibi to ti kọ nipa isẹ atọkọse, ti a mọ si Mẹkaliki.

 

 

 

 

Gbajumọ osere tiata naa si sisẹ bii Mẹkaliki fun ọdun mẹtala gbako nileesẹ to n pese omi, water corporation.

ÌRÒYÌN ÌṢÁÁJÚ:

Eyii ni nnkan Meedogun to gbọdọ mọ nípa Taiwo Hassan Babatunde Ogogo, gbajumo osere tiata to dára ilẹ̀

*Sẹ́nétọ̀ àti oludije fún ipò Gómìnà ni ipinlẹ Ogún, Sẹ́nétọ̀ Olamilekan Adeola Yayi tí sọ̀rọ̀ ibanikedun lórí ikú Ogogo, pé a gbìyànjú láti doola ẹ̀mí Ogogo ṣugbọn…..

Ogogo bẹrẹ isẹ tiata lọdun 1981 ni kete to bẹrẹ isẹ mẹkaliki, to si kuro lẹnu isẹ mẹkaliki nileesẹ Water Corporation lọdun 1994, ko le gbajumọ isẹ tiata to yan laayo.

Alhaji Taiwo Hassan Ogogo ṣáájú kí Ọlọjọ tó dé

Agba osere naa ti gba oniruuru ami ẹyẹ nidi isẹ tiata, to si tun gba ami ẹyẹ ipa to ko ninu ere Anikulapo, tii se Alaafin Oyo.

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *

OJB MEDIA HUB is a premier online news platform delivering accurate, timely and unbiased new accross Nigeria and the world.