Orísun: OJB News Yoruba | Akọroyin: Abidemi Eniola, Èkó | Olootu: Lekan Lawal | Ojú-òpó: OJB Media Hub | Ọjọ Ọjọbọ, 10, Oṣù Kẹ̀sán 2026 | ojbmediashub.com.ng | +2348066952410

Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ayọ̀ àti ìgbéraga bo ojú ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọmọ Yorùbá lónìí ní Èkó bí ó ti lé ní ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá (10,000) ènìyàn ti darapọ̀ mọ́ ẹgbẹ́ Iru Ekun nígbà tí Jagun Jagun Yorùbá nni, Chief Sunday Adeyemo (Sunday Igboho) ṣe ìfilọ́lẹ̀ ẹ̀ka aṣẹ Ìpínlẹ̀ Èkó ti Iru Ekun Security Network.
Ìpàdé ńlá tí ó kún fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọmọ Yorùbá ni a ṣe ní pápá ìṣeré ní Èkó, níbi tí Chief Sunday Igboho ti sọ̀rọ̀ sí àwọn ọmọ ẹgbẹ́ tuntun pẹ̀lú ọkàn tó kún fún ìfẹ́ ilẹ̀ Yorùbá.

Nínú ọ̀rọ̀ rẹ̀, ó sọ pé:
“Àwa ọmọ Oodua, a kì í ṣe ọmọ àlè. Ilẹ̀ Yorùbá gbọ́dọ̀ ní òmìnira kúrò lọ́wọ́ ọdaran, jíjí àti apanilẹ́rìn.”
Ohun tó mú kí ayọ̀ pọ̀ sí i ni pé ẹnìkan lára àwọn olólùfẹ́ ilẹ̀ Yorùbá ti fi ilẹ̀ kan tí ó wà ní Ikeja fún ẹgbẹ́ náà láti kọ́ ọ́fíìsì wọn ní Èkó. Èyí yóò jẹ́ olú-ilé-iṣẹ́ fún àwọn iṣẹ́ ààbò Iru Ekun ní Ìpínlẹ̀ Èkó.

Chief Igboho tẹnu mọ́ ọn pé Iru Ekun kì í ṣe fún ìjà, bí kò ṣe fún ààbò ilẹ̀ Yorùbá, láti rí i dájú pé àwọn àgbẹ̀, obìnrin, ọmọdé àti gbogbo ọmọ Yorùbá lè sùn pẹ̀lú ojú méjèèjì ní ilé wọn.
ÌRÒYÌN ÌṢÁÁJÚ:
Àwọn ọmọ ẹgbẹ́ tuntun tí wọ́n wọ aṣọ dúdú tí wọ́n kọ́ “Iru Ekun” sí, fi ìdùnnú hàn pé wọ́n ti múra tán láti dáàbò bo ilẹ̀ Yorùbá.
Kí ni Iru Ekun? Iru Ekun ni ẹgbẹ́ ààbò tí àwọn ọmọ Yorùbá dá sílẹ̀ láti dáàbò bo ilẹ̀ Yorùbá kúrò lọ́wọ́ bandit àti apanilẹ́rìn.
Iṣẹ́ náà ṣì ń lọ lọ́wọ́ ní Èkó.
© OJB News Yorùbá | Ìròyìn Tó Dájú, Èdè Yorùbá Pọ́nbẹlẹ́

One thought on “ẸGBẸ́ẸGBẸ̀RÚN ÈÈYÀN DARAPỌ MỌ ÀJỌ IRÚ ẸKÙN BI SUNDAY IGBOHO ṢE ṢE ÌFILỌ́LẸ̀ ẸKA T’IPINLẸ ÈKÓ”